Biblia Todo Logo
Bìoball air-loidhne

- Sanasan -




Numeri 26:11 - Yoruba Bible

11 Ṣugbọn àwọn ọmọ Kora kò kú.

Faic an caibideil Dèan lethbhreac

Bibeli Mimọ

11 Ṣugbọn awọn ọmọ Kora kò kú.

Faic an caibideil Dèan lethbhreac

Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní

11 Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.

Faic an caibideil Dèan lethbhreac




Numeri 26:11
19 Iomraidhean Croise  

Meraiotu bí Amaraya, Amaraya sì bí Ahitubu.


Ṣalumu ọmọ Kore, ọmọ Ebiasafu, ọmọ Kora ati àwọn ará ilé baba rẹ̀. Gbogbo ìdílé Kora ni alabojuto iṣẹ́ ìsìn ninu tẹmpili ati olùṣọ́ ẹnu ọ̀nà àbáwọlé àgọ́, gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti jẹ́ alabojuto Àgọ́ OLUWA ati olùṣọ́ ẹnu ọ̀nà àbáwọlé rẹ̀.


Bí ọkàn àgbọ̀nrín tií máa fà sí odò tí omi rẹ̀ tutù, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń fà sí ọ, Ọlọrun.


Ọlọrun, a ti fi etí wa gbọ́, àwọn baba wa sì ti sọ fún wa, nípa àwọn ohun tí o ṣe nígbà ayé wọn, àní, ní ayé àtijọ́:


Èrò rere kan ń gbé mi lọ́kàn, mò ń kọ orin mi fún ọba ahọ́n mi dàbí gègé akọ̀wé tó mọṣẹ́.


Ọlọrun ni ààbò ati agbára wa, olùrànlọ́wọ́ tí ó wà nítòsí nígbà gbogbo, ní ìgbà ìpọ́njú.


Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; ẹ kọ orin ayọ̀, ẹ hó sí Ọlọrun.


OLUWA tóbi, ó sì yẹ kí á máa yìn ín lọpọlọpọ ní ìlú Ọlọrun wa.


Ẹ gbọ́, gbogbo orílẹ̀-èdè! Ẹ dẹtí sílẹ̀, gbogbo aráyé,


OLUWA, Ọlọrun Alágbára ti sọ̀rọ̀: ó ké sí gbogbo ayé láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn.


Kora bí ọmọkunrin mẹta: Asiri, Elikana ati Abiasafu; àwọn ni ìdílé Kora.


Àwọn eniyan náà bá kúrò ní agbègbè àgọ́ àwọn Kora ati Datani ati Abiramu. Datani ati Abiramu pẹlu aya ati àwọn ọmọ wọn jáde wá sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ wọn.


ó yanu, ó sì gbé wọn mì, ati àwọn ati ìdílé wọn, ati ohun ìní wọn. Ilẹ̀ sì gbé Kora mì pẹlu àwọn eniyan rẹ̀ ati gbogbo ohun ìní wọn.


Gbogbo wọn, ati ohun ìní wọn, ati àwọn eniyan wọn, lọ sí ipò òkú láàyè, ilẹ̀ panudé, wọ́n sì ṣègbé kúrò láàrin ìjọ eniyan Israẹli.


Ó sì sọ fún Kora ati àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀ pé, “Ní ọ̀la OLUWA yóo fi ẹni tí í ṣe tirẹ̀ tí ó jẹ́ ẹni mímọ́ hàn. Ẹni tí OLUWA bá sì yàn ni yóo mú kí ó súnmọ́ òun.


Àwọn ọmọ Simeoni ní ìdílé-ìdílé nìwọ̀nyí: ìdílé Nemueli, ìdílé Jamini, ati ìdílé Jakini;


ati ohun tí ó ṣe sí Datani ati Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, ọmọ ọmọ Reubẹni. Ẹ ranti bí ilẹ̀ ti lanu, tí ó sì gbé wọn mì ati àwọn ati gbogbo ìdílé wọn, ati àgọ́ wọn, ati gbogbo iranṣẹ ati ẹran ọ̀sìn wọn, láàrin gbogbo Israẹli.


“Ẹ kò gbọdọ̀ pa baba dípò ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ sì ni ẹ kò gbọdọ̀ pa ọmọ dípò baba, olukuluku ni yóo kú fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó bá dá.


Lean sinn:

Sanasan


Sanasan