Biblia Todo Logo
Bìoball air-loidhne

- Sanasan -

O. Daf 41 - Yoruba Bible


Adura Ẹni tí ń Ṣàìsàn

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń ro ti àwọn aláìní: OLUWA yóo gbà á ní ọjọ́ ìpọ́njú.

2 OLUWA yóo máa ṣọ́ ọ, yóo sì dá a sí. Yóo ní ayọ̀ ní ilẹ̀ náà; OLUWA kò ní fi í lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

3 Nígbà tí ó bá wà ní ìdùbúlẹ̀ àìsàn, OLUWA yóo fún un lókun; ní àkókò àìlera OLUWA yóo wo gbogbo àrùn rẹ̀ sàn.

4 Mo ní, “OLUWA, ṣàánú mi kí o sì wò mí sàn; mo ti ṣẹ̀ ọ́.”

5 Àwọn ọ̀tá mi ń ro ibi sí mi, wọ́n ń wí pé, “Nígbà wo ni yóo kú, tí orúkọ rẹ̀ yóo parẹ́?”

6 Tí ọ̀kan bá wá bẹ̀ mí wò, ọ̀rọ̀ tí kò lórí, tí kò nídìí ni yóo máa sọ; bẹ́ẹ̀ ni ninu ọkàn rẹ̀, èrò ibi ni yóo máa gbà. Nígbà tí ó bá jáde, yóo máa rò mí kiri.

7 Gbogbo àwọn tí ó kórìíra mi jọ ń sọ̀rọ̀ wújẹ́wújẹ́ nípa mi; ohun tó burú jùlọ ni wọ́n ń rò sí mi.

8 Wọ́n ń wí pé, “Àìsàn burúkú ti gbé e dálẹ̀; kò ní dìde mọ́ níbi tí ó dùbúlẹ̀ sí.”

9 Àní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi tí mo gbẹ́kẹ̀lé, tí ó ń jẹun nílé mi, ó ti kẹ̀yìn sí mí.

10 Ṣugbọn, OLUWA, ṣàánú mi; gbé mi dìde, kí n lè san ẹ̀san fún un.

11 Kí n lè mọ̀ pé o fẹ́ràn mi, nígbà tí ọ̀tá kò bá borí mi.

12 O ti gbé mi ró nítorí ìwà pípé mi, o sì fi ẹsẹ̀ mi múlẹ̀ níwájú rẹ títí lae.

13 Ìyìn ni fún OLUWA, Ọlọrun Israẹli, lae ati laelae. Amin! Amin!

Bible Society of Nigeria © 1900/2010

Bible Society of Nigeria
Lean sinn:



Sanasan