Esteri 5:9 - Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní9 Hamani jáde lọ ní ọjọ́ náà pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó rí Mordekai ní ẹnu-ọ̀nà ọba, ó wòye pé kò dìde tàbí kí ó bẹ̀rù ní iwájú òun, inú bí i gidigidi sí Mordekai. Sien die hoofstukYoruba Bible9 Hamani jáde pẹlu ayọ̀ ńlá, ati ìdùnnú. Ṣugbọn nígbà tí ó rí Modekai ní ẹnu ọ̀nà ààfin, tí kò tilẹ̀ mira rárá tabi kí ó wárìrì, inú bí i sí Modekai. Sien die hoofstukBibeli Mimọ9 Nigbana ni Hamani jade lọ li ọjọ na tayọ̀tayọ̀, ati pẹlu inu didùn: ṣugbọn nigbati Hamani ri Mordekai li ẹnu ọ̀na ile ọba pe, kò dide duro, bẹ̃ni kò pa ara rẹ̀ da fun on, Hamani kún fun ibinu si Mordekai. Sien die hoofstuk |